al-Waqi`ah (الوَاقِعَة)

Yoruba:Mikail - Yoruba:Mikail

Chapter 56 • 96 verses • Meccan

← Previous Chapter Next Chapter →
56:1 Nígbà tí Ìṣẹ̀lẹ̀ (Àjíǹde) bá ṣẹlẹ̀,
56:2 - kò sí irọ́ kan nípa ìṣẹ̀lẹ̀ rẹ̀-
56:3 ó máa mú (àwọn kan) wálẹ̀ (sínú Iná), ó sì máa gbé (àwọn kan) sókè (nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra).
56:4 Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní mímìtìtì,
56:5 àti nígbà tí Wọ́n bá fọ́ àwọn àpáta ní fífọ́ wómúwómú,
56:6 - wọ́n sì máa di eruku àfẹ́dànù -
56:7 ẹ̀yin sì máa jẹ́ oríṣi mẹ́ta.[1]
56:8 Àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún, kí ni (ó máa ti dára tó fún) àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún?
56:9 Àwọn èrò ọwọ́ òsì, kí ni (ó máa ti burú tó fún) àwọn èrò ọwọ́ òsì?
56:10 Àwọn aṣíwájú sì ni àwọn aṣíwájú.
56:11 Àwọn wọ̀nyẹn ni alásùn-únmọ́ (Allāhu)
56:12 nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.
56:13 Wọ́n pọ̀ nínú àwọn ẹni àkọ́kọ́.
56:14 Wọ́n sì kéré nínú àwọn ẹni Ìkẹ́yìn.
56:15 (Wọn yóò wà) lórí ìtẹ́ tí wọ́n fi góòlù hun.
56:16 Wọn yóò rọ̀gbọ̀kú sórí rẹ̀, wọn sì máa dojú kọra wọn.
56:17 Àwọn ọ̀dọ́kùnrin tí kò níí darúgbó yó sì máa lọ bọ̀ láààrin wọn
56:18 pẹ̀lú àwọn ife omi, ohun ìrọmi fẹ̀ǹfẹ̀ àti ife ọtí aládùn láti inú odò kan tó ń ṣàn (káà kiri ọ̀dọ̀ wọn).
56:19 Kò níí fọ́ wọn lórí; kò sì níí mú wọn húnrìrà.
56:20 Èso tí wọn yóò máa ṣẹ̀ṣà nínú rẹ̀ (tún wà fún wọn).
56:21 Àti ẹran ẹyẹ, èyí tí wọ́n ń fẹ́ (yó wà fún wọn).
56:22 Àwọn obìnrin ẹlẹ́yinjú ẹgẹ́ (tún wà fún wọn).
56:23 Wọ́n dà bí àlúùúlù (òkúta olówó-iye-bíye) tí wọ́n fi pamọ́ sínú apó rẹ̀.
56:24 (Ìwọ̀nyí ni) ẹ̀san fún ohun tí wọ́n ń ṣe níṣẹ́.
56:25 Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ àti ọ̀rọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.
56:26 Àyàfi ọ̀rọ̀ àlàáfíà, àlàáfíà.
56:27 Àwọn èrò ọwọ́ ọtún, kí ni (ó máa ti dára tó fún) àwọn èrò ọwọ́ ọtún?
56:28 (Wọn yóò wà) ní ìdí igi tí kò ní ẹ̀gún,
56:29 àti ọ̀gẹ̀dẹ̀ tó so jìgbìnnì,
56:30 àti ibòji tó gbòòrò,
56:31 àti omi tó ń ṣàn láì dáwọ́ dúró,
56:32 àti ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ èso,
56:33 tí kò níí já (ní ọ̀dọ̀ wọn), kò sì níí dèèwọ̀ (fún wọn).
56:34 (Wọ́n máa wà lórí) ìtẹ́ tí wọ́n gbé sókè.
56:35 Dájúdájú Àwa dá (àwọn obìnrin Ọgbà Ìdẹ̀ra) ní ẹ̀dá kan (tó yàtọ̀ sí tayé).
56:36 A sì ṣe wọ́n ní wúńdíá,
56:37 olólùfẹ́ ọkọ. Wọ́n sì dọ́gba ní ọjọ́ orí.
56:38 (Wọ́n wà) fún àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
56:39 Wọ́n pọ̀ nínú àwọn ẹni àkọ́kọ́.
56:40 Wọ́n tún pọ̀ nínú àwọn ẹni Ìkẹ́yìn.[1]
56:41 Àwọn èrò ọwọ́ òsì, kí ni (ó máa ti burú tó fún) àwọn èrò ọwọ́ òsì?
56:42 (Wọn yóò wà) nínú atẹ́gùn gbígbóná (iná) àti omi tó gbóná parí,
56:43 àti ní abẹ́ ibòji eléèéfín dúdú,
56:44 kò tutù, kò sì dára.
56:45 Dájúdájú wọ́n ti jẹ́ onígbẹdẹmukẹ ṣíwájú ìyẹn.
56:46 Wọ́n sì máa ń ṣoríkunkun lórí ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.
56:47 Wọ́n sì máa ń wí pé: “Ṣé nígbà tí a bá di òkú, tí a sì di erùpẹ̀ àti egungun, ǹjẹ́ Wọn yóò tún gbé wa dìde ni?
56:48 Ṣé àti àwọn bàbá wa, àwọn ẹni àkọ́kọ́?”
56:49 Sọ pé: “Dájúdájú àwọn ẹni àkọ́kọ́ àti àwọn ẹni Ìkẹ́yìn,
56:50 dájúdájú A óò kó wọn jọ papọ̀ ní àkókò ọjọ́ kan tí A ti mọ̀.”
56:51 Lẹ́yìn náà, dájúdájú ẹ̀yin olùṣìnà, olùpe-òdodo-nírọ́,
56:52 dájúdájú ẹ̀yin máa jẹ nínú igi zaƙƙūm (igi iwọ).
56:53 Ikùn yín sì máa kún bámúbámú fún (jíjẹ) igi náà.
56:54 Ẹ̀yin yó sì máa mu omi tó gbóná parí lé e lórí.
56:55 Ẹ̀yin yóò máa mu ún ní ìmumi ràkúnmí tí òǹgbẹ ń gbẹ.
56:56 Èyí ni n̄ǹkan àlejò wọn ní Ọjọ́ ẹ̀san.
56:57 Àwa l’A ṣẹ̀dá yín. Kí ni kò jẹ́ kí ẹ gbàgbọ́ ní òdodo!
56:58 Ẹ sọ fún Mi nípa àtọ̀ tí ẹ̀ ń dà jáde (sínú àpòlùkẹ́),
56:59 ṣé ẹ̀yin lẹ ṣẹ̀dá rẹ̀ ni tàbí Àwa l’A ṣẹ̀dá rẹ̀?
56:60 Àwa l’A yan kádàrá (ọjọ́) ikú fún gbogbo yín. Kò sì sí ẹni tó lè dá Wa lágara
56:61 láti yí irú yín padà (láti inú erùpẹ̀ sí alààyè), kí á sì ṣẹ̀dá yín (ní ọ̀tun) sínú ohun tí ẹ kò mọ̀ (nínú àwọn ìrísí).
56:62 Ẹ kúkú mọ ìṣẹ̀dá àkọ́kọ́ (pé láti ibi àìsí ni ẹ ti di alààyè), ẹ kò ṣe lo ìrántí?
56:63 Ẹ sọ fún Mi nípa n̄ǹkan tí ẹ̀ ń gbìn sínú ilẹ̀,
56:64 ṣé ẹ̀yin l’ẹ̀ ń jẹ́ kí ó hù jáde tàbí Àwa l’À ń jẹ́ kí ó hù jáde?
56:65 Tí A bá fẹ́ ni, Àwa ìbá sọ ọ́ di gbígbẹ, ẹ̀yin yó sì máa ṣèèmọ̀ (tí ẹ óò máa ká àbámọ̀).
56:66 (Ẹ̀yin yó sì wí pé:) “Dájúdájú àwa ti di onígbèsè.”
56:67 (Àwọn mìíràn yó sì wí pé:) “Rárá o! Wọ́n ṣe ìkórè oko ní èèwọ̀ fún wa ni.”
56:68 Ẹ sọ fún mi nípa omi tí ẹ̀ ń mu,
56:69 ṣé ẹ̀yin l’ẹ̀ ń sọ̀ ọ́ kalẹ̀ láti inú ẹ̀ṣújò ni tàbí Àwa l’À ń sọ̀ ọ́ kalẹ̀?
56:70 Tí A bá fẹ́ ni, Àwa ìbá ṣe é ní omi tó móró. Ẹ ò ṣe máa dúpẹ́?
56:71 Ẹ sọ fún Mi nípa iná tí ẹ̀ ń dá,
56:72 ṣé ẹ̀yin l’ẹ ṣẹ̀dá igi rẹ̀ ni tàbí Àwa ni Aṣẹ̀dá?
56:73 Àwa ṣe iná ayé ní ìrántí (fún Iná ọ̀run) àti n̄ǹkan èlò fún àwọn onírìn-àjò.
56:74 Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Atóbi.
56:75 Nítorí náà, Mò ń fi àwọn àyè tí ìkọ̀ọ̀kan gbólóhùn al-Ƙur’ān wà nínú sánmọ̀ búra.[1]
56:76 Dájúdájú ìbúra ńlá ni, tí ẹ bá mọ̀.
56:77 Dájúdájú (al-Ƙur’ān) ni n̄ǹkan kíké alápọ̀n-ọ́nlé.
56:78 Ó wà nínú Tírà kan tí wọ́n ń fi ààbò bò (ìyẹn Laohul-Mahfūṭḥ).
56:79 Kò sí ẹni tó lè fọwọ́ kàn án (ní ọ̀dọ̀ Allāhu) àfi àwọn ẹni mímọ́ (ìyẹn, àwọn mọlāika).
56:80 Wọ́n sọ al-Ƙur’ān kalẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
56:81 Nítorí náà, ṣé ọ̀rọ̀ (al-Ƙur’ān) yìí l’ẹ̀ ń pè ní irọ́?
56:82 Ẹ sì ń sọ ìdúpẹ́ arísìkí yín di pé dájúdájú ẹ̀ ń pe òdodo ní irọ́.[1]
56:83 Kí ni ó máa ti rí (fún yín) nígbà tí ẹ̀mí (yín) bá dé ọ̀nà ọ̀fun,
56:84 tí ẹ̀yin yó sì máa wò bọ̀ọ̀ nígbà yẹn?
56:85 Àwa sì súnmọ́ ọn ju ẹ̀yin lọ, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò ríran.[1]
56:86 Ẹ̀yin kò ṣe jẹ́ ẹni tí A ò níí gbẹ̀san lára rẹ̀,
56:87 kí ẹ sì dá (ẹ̀mí tí ó fẹ́ bọ́) padà, tí ẹ bá jẹ́ olódodo.
56:88 Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn alásùn-únmọ́ (Wa),
56:89 ìsinmi, èsè tó dára àti Ọgbà Ìdẹ̀ra (ni tirẹ̀).
56:90 Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún,
56:91 àlàáfíà ni fún ọ láààrin àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
56:92 Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn olùpe-òdodo-nírọ́, àwọn olùṣìnà,
56:93 n̄ǹkan àlejò (wọn) ni omi tó gbóná parí
56:94 àti wíwọ inú iná Jẹhīm.
56:95 Dájúdájú èyí, òhun ni òdodo tó dájú.
56:96 Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Atóbi.