an-Nazi`at (النَّازِعَات)

Yoruba:Mikail - Yoruba:Mikail

Chapter 79 • 46 verses • Meccan

← Previous Chapter Next Chapter →
79:1 Allāhu fi àwọn mọlāika tó ń fi ọ̀nà èle gba ẹ̀mí àwọn aláìgbàgbọ́ búra.
79:2 Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń fi ọ̀nà ẹ̀rọ̀ gba ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo búra.
79:3 Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń yára gágá níbi àṣẹ Rẹ̀ búra.
79:4 Ó tún fi àwọn mọlāika tó máa ṣíwájú ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo wọnú Ọgbà Ìdẹ̀ra tààrà búra.
79:5 Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń ṣètò nínú sánmọ̀ àti ilé ayé pẹ̀lú àṣẹ Allāhu búra.
79:6 Ní ọjọ́ tí ìmìtìtì máa mi gbogbo ayé tìtì.[1]
79:7 Ohun tí ó máa tẹ̀lé e máa ṣẹlẹ̀ tẹ̀lé e.[1]
79:8 Àwọn ọkàn yóò máa gbọ̀n pẹ̀pẹ̀ ní ọjọ́ yẹn.
79:9 Ojú wọn yó sì wálẹ̀ ní ti ìyẹpẹrẹ.
79:10 Wọn yóò wí pé: “Ṣé Wọ́n tún máa dá wa padà sí ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀mí (bíi tayé ni)?
79:11 Ṣé nígbà tí a ti di eegun tó kẹfun tán?”
79:12 Wọ́n wí pé: “Ìdápadà òfò nìyẹn nígbà náà (fún ẹni tó pè é ní irọ́.)”
79:13 Nítorí náà, igbe ẹyọ kan sì ni.
79:14 Nígbà náà ni wọn yóò bára wọn lórí ilẹ̀ gban̄sasa.
79:15 Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ (Ànábì) Mūsā ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?
79:16 (Rántí) nígbà tí Olúwa rẹ̀ pè é ní àfonúfojì mímọ́, Tuwā.
79:17 Lọ bá Fir‘aon, dájúdájú ó ti tayọ ẹnu-ààlà.
79:18 Kí o sì sọ pé: “Ǹjẹ o máa ṣàfọ̀mọ́ ara rẹ (kúrò nínú àìgbàgbọ́) bí?
79:19 Kí èmi sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́ dé ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ, kí o sì páyà (Rẹ̀).”
79:20 Ó sì fi àmì tó tóbi hàn án.
79:21 (Àmọ́) ó pè é ní òpùrọ́. Ó sì yapa (rẹ̀).
79:22 Lẹ́yìn náà, ó kẹ̀yìn sí i. Ó sì ń ṣiṣẹ́ (takò ó).
79:23 Ó kó (àwọn ènìyàn) jọ, ó sì ké gbàjarì.
79:24 Ó sì wí pé: “Èmi ni olúwa yín, ẹni gíga jùlọ.”
79:25 Nítorí náà, Allāhu gbá a mú pẹ̀lú ìyà ìkẹ́yìn àti àkọ́kọ́ (nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ ìkẹ́yìn yìí àti àkọ́kọ́).[1]
79:26 Dájúdájú àríwòye wà nínú ìyẹn fún ẹni tó ń páyà (Allāhu).
79:27 Ṣé ẹ̀yin lẹ lágbára jùlọ ní ìṣẹ̀dá ni tàbí sánmọ̀ tí Allāhu mọ?
79:28 Allāhu gbé àjà rẹ̀ ga sókè. Ó sì ṣe é ní pípé tó gún régé.
79:29 Ó ṣe òru rẹ̀ ní dúdú. Ó sì fa ìyálẹ̀ta rẹ̀ yọ jáde.
79:30 Àti ilẹ̀, Ó tẹ́ ẹ pẹrẹsẹ lẹ́yìn ìyẹn.[1]
79:31 Ó mú omi rẹ̀ àti irúgbìn rẹ̀ jáde láti inú rẹ̀.
79:32 Àti àwọn àpáta, Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ ṣinṣin.
79:33 Ìgbádùn ni fún yín àti fún àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.
79:34 Ṣùgbọ́n nígbà tí ìparun ńlá bá dé,
79:35 ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò rántí ohun tó ṣe níṣẹ́.
79:36 Wọ́n sì máa fi Iná hàn kedere fún (gbogbo) ẹni tó ríran.
79:37 Nítorí náà, ní ti ẹni tó tayọ ẹnu-ààlà,
79:38 tí ó tún gbé àjùlọ fún ìṣẹ̀mí ayé,
79:39 dájúdájú iná Jẹhīm, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
79:40 Ní ti ẹni tí ó páyà ìdúró níwájú Olúwa rẹ̀, tí ó tún kọ ìfẹ́-inú fún ẹ̀mí (ara rẹ̀),
79:41 dájúdájú Ọgbà Ìdẹ̀ra, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
79:42 Wọ́n ń bi ọ́ léèrè nípa Àkókò náà pé: “Ìgbà wo l’ó máa ṣẹlẹ̀?”
79:43 Níbo ni ìwọ wà sí ìmọ̀ rẹ̀ ná?[1]
79:44 Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni òpin ìmọ̀ nípa rẹ̀ wà.
79:45 Ìwọ kúkú ni olùkìlọ̀ fún ẹni tó ń páyà rẹ̀.
79:46 Ní ọjọ́ tí wọ́n máa rí i, wọn máa dà bí ẹni pé wọn kò gbé ilé ayé tayọ ìrọ̀lẹ́ tàbí ìyálẹ̀ta (ọjọ́) kan.