al-Layl (اللَّيْل)

Yoruba:Mikail - Yoruba:Mikail

Chapter 92 • 21 verses • Meccan

← Previous Chapter Next Chapter →
92:1 Allāhu fi alẹ́ nígbà tí (ilẹ̀) bá ṣú búra.
92:2 Ó tún fi ọ̀sán nígbà tí (ọ̀sán) bá pọ́n búra.
92:3 Ó tún fi Ẹni tí Ó dá akọ àti abo búra.[1]
92:4 Dájúdájú ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni iṣẹ́ yín.
92:5 Ní ti ẹni tí ó bá tọrẹ, tí ó sì bẹ̀rù (Allāhu),
92:6 (tí) ó tún pe ẹ̀san rere (Ọgbà Ìdẹ̀ra) ní òdodo,
92:7 A sì máa ṣe iṣẹ́ rere ní ìrọ̀rùn fún un.
92:8 Ní ti ẹni tí ó bá yahun, tí ó sì rí ara rẹ̀ lẹ́ni tó rọrọ̀ tayọ ẹ̀san ọ̀run,
92:9 (tí) ó tún pe ẹ̀san rere (Ọgbà Ìdẹ̀ra) ní irọ́,
92:10 A sì máa ṣe iṣẹ́ aburú ní ìrọ̀rùn fún un.
92:11 Dúkìá rẹ̀ kò sì níí rọ̀ ọ́ lọ́rọ̀ nígbà tí ó bá parun, tí ó já bọ́ (sínú Iná).
92:12 Dájúdájú tiWa ni (láti ṣàlàyé) ìmọ̀nà.
92:13 Àti pé dájúdájú tiWa ni ọ̀run àti ayé.
92:14 Nítorí náà, Mo ti fi Iná tó ń jò fòfò kìlọ̀ fún yín.
92:15 Kò sí ẹni tí ó máa wọ inú rẹ̀ àfi olórí burúkú,
92:16 ẹni tí ó pe òdodo ní irọ́, tí ó sì kẹ̀yìn sí i.
92:17 Wọ́n sì máa gbé (Iná) jìnnà sí olùbẹ̀rù (Allāhu),
92:18 ẹni tó ń fi dúkìá rẹ̀ tọrẹ, tí ó ń ṣàfọ̀mọ́ (rẹ̀).
92:19 Kò sì sí oore ìdẹ̀ra kan tí (ó ní lọ́kàn) láti gbà ní ẹ̀san ní ọ̀dọ̀ ẹnikẹ́ni,
92:20 bí kò ṣe pé láti fi wá ojú rere Olúwa rẹ̀, Ẹni Gíga jùlọ.
92:21 Láìpẹ́ ó sì máa yọ́nú (sí ẹ̀san rere rẹ̀).