82:1
Nígbà tí sánmọ̀ bá fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,[1]
82:2
àti nígbà tí àwọn ìràwọ̀ bá já bọ́ káàkiri,
82:3
àti nígbà tí àwọn ibúdò bá ṣàn jára wọn,
82:4
àti (nígbà tí A bá ta ilẹ̀ sókè), tí A sì mú àwọn òkú jáde (láàyè) láti inú àwọn sàréè,
82:5
(nígbà náà ni) ẹ̀mí kọ̀ọ̀kan yóò mọ ohun tí ó tì síwájú (nínú iṣẹ́ rẹ̀) àti ohun tí ó fi sẹ́yìn (nínú orípa iṣẹ́ rẹ̀).
82:6
Ìwọ ènìyàn, kí ni ó tàn ọ́ jẹ nípa Olúwa rẹ, Alápọ̀n-ọ́nlé,
82:7
Ẹni t’Ó ṣẹ̀dá rẹ? Ó ṣẹ̀dá rẹ̀ ní pípé. Ó sì mú ọ dọ́gba jalẹ̀ léèyàn.
82:8
Ó to ẹ̀yà ara rẹ papọ̀ sínú èyíkéyìí àwòrán tí Ó fẹ́.
82:9
Rárá! Bí kò ṣe pé ẹ̀ ń pe Ọjọ́ ẹ̀san ní irọ́.
82:10
Dájúdájú àwọn ẹ̀ṣọ́ sì wà ní ọ̀dọ̀ yín.
82:11
(Wọ́n jẹ́) alápọ̀n-ọ́nlé, òǹkọ̀wé-iṣẹ́ ẹ̀dá.
82:12
Wọ́n mọ ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.
82:13
Dájúdájú àwọn ẹni rere yóò kúkú wà nínú ìgbádùn.
82:14
Dájúdájú àwọn ẹni ibi yó sì kúkú wà nínú iná Jẹhīm.
82:15
Wọn yóò wọ inú rẹ̀ ní Ọjọ́ ẹ̀san.
82:16
Wọn kò sì níí kúrò nínú rẹ̀.
82:17
Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ Ọjọ́ ẹ̀san?
82:18
Lẹ́yìn náà, kí ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ Ọjọ́ ẹ̀san?
82:19
(Ọjọ́ ẹ̀san ni) ọjọ́ tí ẹ̀mí kan kò níí kápá kiní kan fún ẹ̀mí kan. Gbogbo àṣẹ ọjọ́ yẹn sì ń jẹ́ ti Allāhu.