at-Tariq (الطَّارِق)

Yoruba:Mikail - Yoruba:Mikail

Chapter 86 • 17 verses • Meccan

← Previous Chapter Next Chapter →
86:1 (Allāhu) fi sánmọ̀ àti Tọ̄riƙ búra.
86:2 Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ Tọ̄riƙ?
86:3 Ìràwọ̀ tí ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ń tàn ròrò (ní alẹ́ ni).
86:4 Kò sí ẹ̀mí kan àfi kí ẹ̀ṣọ́ kan wà fún un (nínú àwọn mọlāika).
86:5 Nítorí náà, kí ènìyàn wòye sí ohun tí A fi ṣẹ̀dá rẹ̀.
86:6 Wọ́n ṣẹ̀dá rẹ̀ láti inú omi tó ń tú jáde kọ̀ọ́kọ̀ọ́.
86:7 Ó ń jáde láti ààrin ìbàdí ọkùnrin àti àwọn ẹfọ́nhà igbá-àyà obìnrin.
86:8 Dájúdájú Allāhu ni Alágbára lóri ìdápadà rẹ̀
86:9 ní ọjọ́ tí wọ́n máa ṣe àyẹ̀wò àwọn (iṣẹ́) àṣepamọ́.
86:10 Nígbà náà, kò níí sí agbára tàbí alárànṣe kan fún un.
86:11 Allāhu fi sánmọ̀ tó ń rọ òjò ní ọdọọdún búra.
86:12 Ó tún fi ilẹ̀ tó ń sán kànkàn (fún híhùjáde èso) búra.
86:13 Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ọ̀rọ̀-ìpínyà (láààrin òdodo àti irọ́).
86:14 Kì í sì ṣe àwàdà.
86:15 Dájúdájú wọ́n ń déte gan-an.
86:16 Èmi náà sì ń déte gan-an.[1]
86:17 Nítorí náà, lọ́ra fún àwọn aláìgbàgbọ́. Lọ́ wọn lára sẹ́ fún ìgbà díẹ̀.